
Play all audios:
YINKA ODUMAKIN: WO ÀWỌN OHUN TÓ YẸ KÍ O MỌ̀ NÍPA AGBẸNUSỌ AFENIFERE TÓ DOLÓÒGBÉ 3 Ìgbé 2021 AARỌ ỌJỌ KẸTA, OṢU KẸRIN, ỌDUN 2021 NI IROYIN GBODE PE ỌKAN NINU AWỌN ASAAJU ẸGBẸ ỌMỌ BIBI ILẸ
YORUBA, OLOYE YINKA ODUMAKIN TI DAGBERE FAYE. Odumakin, nigba aye rẹ ni agbẹnusọ fun ẹgbẹ Afenifere, to n sọrọ lorukọ ẹya Yoruba lori awọn isẹlẹ to n waye nilẹ wa. Lati igba ti iroyin naa ti
jade ni ọpọ awọn eekan ilu atawọn oloṣelu ti bẹrẹ si n fi ọrọ ẹdun lede lori iku akọni ọhun. * Ẹ̀yà ara bí ẹ̀mí mi ló kú - Joe Okei, ìyàwó olóògbé Yinka Odumakin * Ìwádìí rèé lórí ìdí tílé
ẹjọ́ fi gba onídùróó Wòlìí Genesis lọ́gbà ẹ̀wọ̀n * Ogún ódún ni mo wà nígbà tí mo kọ́kọ́ ṣe ìgbéyàwó, ṣùgbọ́n ó túká - Don Jazzy * Irọ́ ni o, kìí ṣe Boko Haram ló já ọkọ̀ òfúrufú ọmọgun
Alpha Jet bọ́ - NAF * Èèmọ̀! West Brom fi omi àbùkù wẹ̀ fún Chelsea lọ́sàn án gangan nílé wọn * Kí ló fa ìjà rọ̀fọ̀rọ́fọ̀ láàrin Toyin Abraham àti olólùfẹ́ rẹ̀ lórí ayélujára? * Mo ti padà
sí ẹ̀sìn òwúrọ̀ mi o! Ẹ̀ gb'Ọ́lọ́hun tóbi - Yomi Fabiyi Awọn ohun to yẹ ki o mọ nipa Yinka Odumakin ree. * Ọjọ kẹwaa, ninu oṣu kejila ni wọn bi Yinka Odumakin * O kawe gboye ni fasiti
Obafemi Awolowo, niluu Ile Ife lọdun 1989 * Lasiko to jẹ akẹkọọ ni fasiti, oun ni agbẹnusọ fun ẹgbẹ awọn akẹkọọ, iyẹn SUG * O bẹrẹ iṣẹ akọroyin nileeṣẹ iwe iroyin Punch to wa niluu Eko,
lẹyin naa lo darapọ mọ iwe iroyin Guardian * Akọni ọhun wa lara awọn to gbogun ti ijọba ologun labẹ iṣakoso ọgagun Sani Abacha lẹyin to da ibo Aarẹ nu lọjọ kejila, oṣu Kẹfa, ọdun 1993 ti
gbogbo eeyan gbagbọ pe o gbe oloogbe MKO Abiola wọle sipo Aarẹ * Odumakin kopa ninu ipade apapọ orilẹ-ede Naijiria, National Confab, to waye niluu Abuja lọdun 2014 * Aarẹ Muhammadu Buhari
yan Odumakin gẹgẹ bii agbẹnusọ ikọ ipolongo rẹ nigba to n mura idibo Aarẹ lọdun 2011 * Odamakin gbe ajafẹtọ bii tirẹ ni iyawo, iyẹn Joe Okei-Odumakin, wọn si jọ wa titi di akoko ti ọlọjọ de
* Ko tan sibẹ, Odumakin tun ṣiṣẹ gẹgẹ bii akọwe ẹgbẹ ajafẹtọ Save Nigerian Group ti Pasitọ Tunde Bakare ṣagbatẹru rẹ lọdun 2010 * Titi di igba ti ọlọjọ de, Odumakin ni agbẹnusọ fun ẹgbẹ ọmọ
Yoruba, Afenifere, o si wa lara awọn to n bu ẹnu ẹtẹ lu bii awọn ọdaran darandaran ṣe n pa eeyan kaakiri ilẹ Yoruba _KI LO TI ṢẸLẸ SẸYIN?_ Skip Èyítí A Ń Kà Jùlọ and continue reading ÈYÍTÍ A
Ń KÀ JÙLỌ * Ìdí tí àkọọ́lẹ̀ 'writing' àwọn dókítà ò fi kí n dùn ún wò tí kìí sí yé èèyàn * Wo ìlú tó ti jẹ dandan fún ọkọ láti rà kẹ̀kẹ́ fún ìyàwó kí ìgbeyàwó tó ó le wáyé * Òbí
sọ ọ̀gá ilé-ẹ̀kọ́ di èèrò iléèwòsàn lẹ́yìn tí kò jẹ́ kí ọmọ rẹ̀ jìwèé wò nínú ìdánwò WAEC l'Akure * Ojú mi ni omi ṣe wọ́ ìyàwó àti ọmọ mi lọ, èèyàn mẹ́sàn-án ni èmi nìkan pàdánù nínú
ẹ̀kún omi Mokwa' End of Èyítí A Ń Kà Jùlọ Ọ̀PỌ̀ ỌMỌ YORÙBÁ Ń ṢÈDÁRÒ YINKA ODUMAKIN TÓ DI OLÓÒGBÉ Yoruba ni bi ọdẹ ba ku, ọdẹ ni yoo se oro lẹyin ọdẹ, ba si ku la dere, eeyan ko sunwọn
laaye. Ọpọ ọmọ ilẹ kaarọ oojire lo ti n sedaro iku agba ọmọ Yoruba to jade laye, Oloye Yinka Odumakin. Ile iwosan ẹkọsẹ isegun fasiti ipinlẹ Eko, LASUTH ni Odumakin dakẹ si lasiko aisan
ranpẹ to se e. ÀWỌN IRÒYIN TÌ Ẹ LEÈ NÍ ÌFẸ̀ SÍÍ: * Kí ló fa ìjà rọ̀fọ̀rọ́fọ̀ láàrin Toyin Abraham àti olólùfẹ́ rẹ̀ lórí ayélujára? * Mo kọ láti gba lẹtà ọgá ọlọpàá, kí wọn má fi bọǹbù pa mí
bíi Dele Giwa - Igboho * Ẹkún àti ìdárò gbòde bí ọja páàtì ní Agodi-Gate ní Ibadan ṣe jóná mọ́jú * Àwọn ọ̀nà tá gbà rèé tí orílẹ̀èdè Oduduwa yóò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́ - Gani Adams * Ọ̀daràn
darandaran pàdà sí Igangan, wọ́n gé ọwọ ọ̀gá ilé ẹ̀kọ́ * Ọ̀pọ̀ Sunday Igboho, Nnamdi Kanu ní yóò díde torí ìpànìyàn ojoojúmọ́ * Àwọn èèkàn ọmọ Yorùbá tí ìràwọ̀ Sunday Igboho bo tiwọn mọ́lẹ̀,
ló ń dọdẹ rẹ̀ - Fani-Kayode * "Ikọ̀ Àmọ̀tẹ́kùn, ẹ ṣe pẹ̀lẹ́, ilẹ̀ ń yọ̀" * Gbàjarè! Ọ̀gá ọlọ́pàá fi ìwé ìpè àti géńdé 15 ránṣẹ́ wá mú mi - Sunday Igboho pariwo * Ọ̀pọ̀ Sunday
Igboho, Nnamdi Kanu ní yóò díde torí ìpànìyàn ojoojúmọ́ Gẹgẹ ba se gbọ, ẹka ile iwosan naa, ti wọn ti n tọju awọn eeyan to ni arun Coronavirus ni Odumakin mi kanlẹ si ni idaji ọjọ Abamẹta.
Nigba to n fi idi iku ọrọ rẹ mulẹ fawọn akọroyin, aya oloogbe naa, Ọmọwe Joe Odumakin ni manigbagbe ni iku oloogbe naa jẹ fun oun. "Ọkan lara ẹya ara mi lo lọ yii." YCE NI IKU DORO
Nigba tawọn naa n se idaro ẹni rere to lọ, Ọjọgbọn Banji Akitoye sọ fun BBC Yoruba pe akikanju ọmọ Yoruba lo papoda yii, igi nla lo da nigbo. Lero ti akọwe fun ẹgbẹ agbaagba ilẹ Yoruba,
YCE, Dokita Kunle Olajide ni "Iku doro, erin wo, igi da, Ajanaku sun bi oke, ẹni re lọ." Dokita Olajide ni alafo nla ni iku Odumakin yoo fi silẹ ninu iran Yoruba nitori ipa
akikanju to ko fun ilọsiwaju iran rẹ lasiko to wa loke eepẹ. Akọwe ẹgbẹ agbaagba fun ilẹ Yoruba naa wa gbadura pe ki ọba oke tẹ Odumakin si afẹfẹ rere. AFENIFERE SỌ̀ PE ADANU NLA NI IKU
ODUMAKIN Bakan naa niakọwe ẹgbẹ Afenifere, Basorun Sehinde Arogbofa se apejuwe iku Odumakin bii adanu nla fun ẹgbẹ naa ati orilẹede Naijiria lapapọ. Arogbọfa ni iku Odumakin ba oun lojiji,
to si jẹ ẹsẹ nla to ba oun lairotẹlẹ nitori ẹni to sun mọ oun bii isan ọrun ni. "Yinka ko ba ma lọ lasiko yii nitori ọlọpọlọ pipe ẹda ni, to si maa n mu awọn aba to kun fun ọgbọn wa,
isẹlẹ yii ba mi ninu jẹ pupọ. Arogbofa wa gbadura pe ki Ọlọrun tẹ oloogbe Yinka Odumakin si afẹfẹ rere. ÌRÒYÌN YÀJÓYÀJÓ - YINKA ODUMAKIN, AGBẸNUSỌ FẸ́GBẸ́ AFENIFERE, JÁDE LÁYÉ Iroyin to n tẹ
wa lọwọ ni yajoyajo ti ni ọkan ninu awọn asaaju ẹgbẹ ọmọ bibi ilẹ Yoruba, Oloye Yinka Odumakin ti dagbere faye. Odumakin, nigba aye rẹ ni agbẹnusọ fun ẹgbẹ Afenifere, to n sọrọ lorukọ ẹya
Yoruba lori awọn isẹlẹ to n waye nilẹ wa. Nigba to n fi idi iku oloogbe naa mulẹ fun BBc Yoruba, Ọjọgbọn Banji Akintoye, tii se ọkan lara agbaagba ilẹ Yoruba sọ pe igi nla lo da nigbo
Naijiria. Yinka Odumakin si ni ọkọ gbajumọ ajafẹtọ ẹni lobinrin, Comrade Joe Odumakin.Iku doro, iku sika, iku ti mu ẹni re lọ. A o maa mu ẹkunrẹrẹ iroyin nipa itan igbe aye ati iku oloogbe
Yinka Odumakin wa fun yin laipẹ.